5 Nígbà tí abo kinniun náà rí i pé ọwọ́ tẹ ọmọ òun,ati pé igbẹkẹle òun ti dòfo,ó mú òmíràn ninu àwọn ọmọ rẹ̀,ó tọ́ ọ di ọ̀dọ́ kinniun.
6 Ó ń yan kiri láàrin àwọn kinniun;nítorí ó ti di ọ̀dọ́ kinniun tí ó lágbára,ó kọ́ bí wọn tí ń ṣe ọdẹ,ó sì ń pa eniyan jẹ.
7 Ó wó ilé ìṣọ́ wọn lulẹ̀;ó sọ ìlú wọn di ahoro.Ẹ̀rù ba gbogbo Ilẹ̀ náà, ati gbogbo àwọn tí ń gbé ibẹ̀,nígbà tí wọ́n gbọ́ bíbú rẹ̀.
8 Àwọn orílẹ̀-èdè bá dójú lé e,wọ́n dẹ tàkúté fún un ní gbogbo ọ̀nà,wọ́n da àwọ̀n wọn bò ó,wọ́n sì mú un ninu kòtò tí wọn gbẹ́ fún un.
9 Wọ́n sọ ìwọ̀ sí i nímú,wọ́n gbé e jù sinu àhámọ́,wọ́n sì fà á lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Babiloni.Wọ́n fi sí àtìmọ́lé,kí wọ́n má baà gbọ́ ohùn rẹ̀ mọ́ lórí àwọn òkè Israẹli.
10 Ìyá rẹ dàbí àjàrà inú ọgbàtí a gbìn sí ẹ̀gbẹ́ odò;ó rúwé, ó yọ ẹ̀ka,nítorí ó rí omi lọpọlọpọ.
11 Ẹ̀ka rẹ̀ tí ó lágbárani a fi gbẹ́ ọ̀pá àṣẹ fún àwọn olórí.Ó dàgbà, ó ga fíofío, láàrin àwọn igi igbó.Ó rí i bí ó ti ga, tí ẹ̀ka rẹ̀ sì pọ̀.