1 Ní ọjọ́ kinni, oṣù kẹta, ọdún kọkanla tí a ti wà ní ìgbèkùn, OLUWA bá mi sọ̀rọ̀, ó ní,
2 “Ìwọ ọmọ eniyan, sọ fún Farao, ọba Ijipti, pẹlu ogunlọ́gọ̀ àwọn eniyan rẹ̀ pé,Ta ni ó lágbára tó ọ?
3 Wò ó! Mo fi ọ́ wé igi kedari Lẹbanoni,àwọn ẹ̀ka rẹ̀ lẹ́wà,wọ́n sì ní ìbòòji ó ga fíofío,orí rẹ̀ sì kan ìkùukùu lójú ọ̀run.
4 Omi mú kí ó dàgbà,ibú omi sì mú kí ó ga.Ó ń mú kí àwọn odò rẹ̀ ṣàn yí ibi tí a gbìn ín sí ká.Ó ń mú kí odò rẹ̀ ṣàn lọ síbi gbogbo igi igbó.
5 Nítorí náà, ó ga sókè fíofío, ju gbogbo igi inú igbó lọ.Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ tóbi, wọ́n sì gùn,nítorí ọpọlọpọ omi tí ó ń rí.