4 Ìwà yín yóo mú kí ilẹ̀ tí mo fun yín bọ́ lọ́wọ́ yín; n óo sí sọ yín di ẹrú àwọn ọ̀tá yín ní ilẹ̀ tí ẹ kò mọ̀rí. Ẹ ti mú kí ibinu mi máa jó bí iná, kò sì ní kú títí lae.”
5 OLUWA ní,“Ègún ni fún ẹni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé eniyan,tí ó fi ẹlẹ́ran ara ṣe agbára rẹ̀;tí ọkàn rẹ̀ yipada kúrò lọ́dọ̀ èmi OLUWA.
6 Ó dàbí igbó ṣúúrú ninu aṣálẹ̀,nǹkan rere kan kò lè ṣẹlẹ̀ sí i.Ninu ilẹ̀ gbígbẹ, ninu aṣálẹ̀ ni ó wà,ninu ilẹ̀ iyọ̀ tí ẹnikẹ́ni kò lè gbé.
7 “Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé OLUWA,tí ó fi OLUWA ṣe àgbẹ́kẹ̀lé rẹ̀.
8 Yóo dàbí igi tí a gbìn sí ipa odò,tí ó ta gbòǹgbò kan ẹ̀bá odò.Ẹ̀rù kò ní bà á nígbà tí ẹ̀ẹ̀rùn bá dé,nítorí pé ewé rẹ̀ yóo máa tutù minimini.Kò ní páyà lákòókò ọ̀gbẹlẹ̀,nígbà gbogbo ni yóo sì máa so.
9 “Ọkàn eniyan kún fún ẹ̀tàn ju ohun gbogbo lọ,ìwà ìbàjẹ́ sì kún inú rẹ̀;ta ni ó lè mọ èrò ọkàn eniyan?
10 Èmi OLUWA ni èmi máa ń wádìí èrò eniyan,tí èmi sì máa ń yẹ ọkàn eniyan wò,láti san án fún olukuluku gẹ́gẹ́ bí ìṣe rẹ̀,ati gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”