Jeremaya 21 BM

Àsọtẹ́lẹ̀ nípa Ìṣubú Jerusalẹmu

1 Ọ̀rọ̀ tí Jeremaya gbọ́ lẹ́nu OLUWA nìyí nígbà tí ọba Sedekaya rán Paṣuri, ọmọ Malikaya, ati alufaa Sefanaya, ọmọ Maaseaya, sí i;

2 tí ọba Sedekaya ní, “Ẹ sọ fún Jeremaya pé kí ó bá wa ṣe ìwádìí lọ́dọ̀ OLUWA nípa Nebukadinesari, ọba Babiloni, tí ó gbógun tì wá; bóyá OLUWA yóo ṣe iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún wa, kí Nebukadinesari kó àwọn ọmọ ogun rẹ̀ kúrò ní ilẹ̀ wa.”

3 Jeremaya sọ fun awọn tí wọn rán sí i,

4 kí wọ́n sọ fún Sedekaya pé OLUWA Ọlọrun Israẹli ní, “N óo gba àwọn ohun ìjà tí ó wà lọ́wọ́ yín, tí ẹ fi ń bá ọba Babiloni ati àwọn ará Kalidea tí wọn gbógun tì yín lẹ́yìn odi jà, n óo dá wọn pada sí ààrin ìlú, n óo sì dojú wọn kọ yín.

5 Èmi fúnra mi ni n óo ba yín jà. Ipá ati agbára, pẹlu ibinu ńlá, ati ìrúnú gbígbóná ni n óo fi ba yín jà.

6 N óo fi àjàkálẹ̀ àrùn ńlá kọlu àwọn ará ìlú yìí, ati eniyan ati ẹranko ni yóo sì kú.

7 Lẹ́yìn náà n óo mú Sedekaya ọba Juda, ati àwọn ìjòyè rẹ̀, ati àwọn tí àjàkálẹ̀ àrùn, ogun, ati ìyàn, bá pa kù ní ìlú yìí, n óo fi wọ́n lé Nebukadinesari, ọba Babiloni lọ́wọ́, òun ati àwọn ọ̀tá tí ń wá ọ̀nà láti pa wọ́n. Ọba Babiloni yóo fi idà pa wọ́n, kò ní ṣàánú wọn, kò sì ní dá ẹnikẹ́ni sí.”

8 OLUWA ní, “Sọ fún àwọn eniyan yìí pé èmi OLUWA ni mo la ọ̀nà meji níwájú wọn: ọ̀nà ìyè ati ọ̀nà ikú.

9 Ogun, ìyàn ati àjàkálẹ̀ àrùn yóo pa ẹni tí ó bá dúró sinu ìlú yìí; ṣugbọn ẹni tí ó bá jáde tí ó sì fa ara rẹ̀ fún àwọn ará Kalidea, tí ó gbé ogun tì yín, yóo yè, yóo dàbí ẹni tó ja àjàbọ́.

10 Nítorí pé mo ti dójú lé ìlú yìí láti ṣe ní ibi, kì í ṣe fún rere. Ìlú yìí yóo bọ́ sọ́wọ́ ọba Babiloni, yóo sì dá iná sun ún, èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

Ìdájọ́ lórí Ìdílé Ọba Juda

11 OLUWA ní kí n sọ fún ìdílé ọba Juda pé òun OLUWA ní,

12 “Ẹ̀yin ará ilé Dafidi!Ẹ máa dá ẹjọ́ ẹ̀tọ́ ní òwúrọ̀,ẹ máa gba ẹni tí a jà lólè lọ́wọ́ aninilára,kí ibinu èmi OLUWA má baà ru jáde, nítorí iṣẹ́ ibi yín,kí ó sì máa jó bíi iná,láìsí ẹni tí yóo lè pa á.”

13 OLUWA ní,“Ẹ wò ó, mo dojú ìjà kọ yín,ẹ̀yin tí ẹ̀ ń gbé àfonífojì,tí ó dàbí àpáta tí ó yọ sókè ju pẹ̀tẹ́lẹ̀ lọ,ẹ̀yin tí ẹ̀ ń wí pé,‘Ta ló lè dojú ìjà kọ wá?Àbí ta ló lè wọ inú odi ìlú wa?’

14 N óo jẹ yín níyà gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ yín;èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.N óo dáná sun igbó yín,yóo sì jó gbogbo ohun tí ó wà ní agbègbè yín ní àjórun.”