Jeremaya 20:4-10 BM

4 OLUWA ní, ‘N óo sọ ọ́ di ìpayà fún ara rẹ ati fún gbogbo àwọn tí wọ́n fẹ́ràn rẹ. Àwọn ọ̀tá yóo fi idà pa wọ́n níṣojú rẹ, n óo fi gbogbo ilẹ̀ Juda lé ọba Babiloni lọ́wọ́. Yóo kó wọn ní ìgbèkùn lọ sí Babiloni, yóo sì fi idà pa wọ́n.

5 Bákan náà, n óo da gbogbo ọrọ̀ ìlú yìí, ati gbogbo èrè iṣẹ́ tí wọ́n ṣe lé àwọn ará Babiloni lọ́wọ́, pẹlu gbogbo nǹkan olówó iyebíye wọn, ati gbogbo ìṣúra àwọn ọba Juda; gbogbo rẹ̀ ni àwọn ọ̀tá wọn, àwọn ará Babiloni yóo fogun kó, wọn yóo sì rù wọ́n lọ sí Babiloni.

6 Ní ti ìwọ Paṣuri, ati gbogbo àwọn ará ilé rẹ, wọn óo ko yín ní ìgbèkùn lọ sí Babiloni. Ibẹ̀ ni ẹ óo kú sí, ibẹ̀ ni wọ́n óo sì sin yín sí; àtìwọ, ati gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ tí ò ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ irọ́ fún.’ ”

7 OLUWA, o tàn mí jẹ, mo sì gba ẹ̀tàn;o ní agbára jù mí lọ, o sì borí mi.Mo di ẹni ẹ̀sín láti àárọ̀ títí di alẹ́,gbogbo eniyan ń fi mí ṣe yẹ̀yẹ́.

8 Gbogbo ìgbà tí mo bá ti sọ̀rọ̀, ni mò ń kígbe pé,“Ogun ati ìparun dé!”Nítorí náà, ọ̀rọ̀ OLUWA tí mò ń kéde sọ mí di ẹni yẹ̀yẹ́ tọ̀sán-tòru.

9 Ṣugbọn nígbàkúùgbà tí mo bá wí pé n kò ní dárúkọ rẹ̀ mọ́,bẹ́ẹ̀ ni n kò ní sọ̀rọ̀ ní orúkọ rẹ̀ mọ́,ọ̀rọ̀ rẹ a máa jó mi ninu bí iná,a sì máa ro mí ninu egungun.Mo gbìyànjú títí pé kí n pa á mọ́ra,ṣugbọn kò ṣeéṣe.

10 Nítorí mò ń gbọ́ tí ọpọlọpọ ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́ pé,“Ìpayà wà lọ́tùn-ún lósì,ẹ lọ fẹjọ́ rẹ̀ sùn.Ẹ jẹ́ kí á fẹjọ́ rẹ̀ sùn.”Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ mi ń wí,tí wọn sì ń retí ìṣubú mi.Wọ́n ń sọ pé,“Bóyá yóo bọ́ sọ́wọ́ ẹlẹ́tàn,ọwọ́ wa yóo sì tẹ̀ ẹ́;a óo sì gbẹ̀san lára rẹ̀.”