2 Èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó wà ninu apẹ̀rẹ̀ kinni dára gbáà, ó dàbí èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó kọ́kọ́ pọ́n. Èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó wà ninu apẹ̀rẹ̀ keji ti rà patapata tóbẹ́ẹ̀ tí kò ṣe é jẹ. p
3 OLUWA bá bi mí pé, “Jeremaya, kí ni o rí?”Mo ní, “Èso ọ̀pọ̀tọ́ ni, àwọn tí ó dára, dára gan-an, àwọn tí kò sì dára bàjẹ́ tóbẹ́ẹ̀ tí wọn kò ṣe é jẹ.”
4 OLUWA tún bá mi sọ̀rọ̀, ó ní,
5 “Ohun tí èmi OLUWA Ọlọrun Israẹli sọ nípa àwọn ará Juda tí wọ́n wà ní ìgbèkùn, àwọn tí mo ti mú kí á kó lẹ́rú láti ibí yìí lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kalidea, ni pé, n óo kà wọ́n sí rere gẹ́gẹ́ bí àwọn èso ọ̀pọ̀tọ́ dáradára wọnyi.
6 N óo fi ojurere wò wọ́n, n óo kó wọn pada wá sí ilẹ̀ yìí. N óo fìdí wọn múlẹ̀, n kò sì ní pa wọ́n run. N óo gbé wọn ró, n kò ní fà wọ́n tu,
7 n óo sì fún wọn ní òye láti mọ̀ pé èmi ni OLUWA. Wọn yóo jẹ́ eniyan mi, èmi náà óo sì jẹ́ Ọlọrun wọn; nítorí tí wọn yóo fi tọkàntọkàn yipada sí mi.”
8 Ṣugbọn ohun tí OLUWA sọ nípa Sedekaya ọba Juda, ati àwọn ìjòyè rẹ̀, ati àwọn ará Jerusalẹmu tí wọ́n kù ní ilẹ̀ yìí, ati àwọn tí wọn ń gbé ilẹ̀ Ijipti, ni pé òun óo ṣe wọ́n bí èso burúkú tí kò ṣe é jẹ.