Jeremaya 30:10-16 BM

10 “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ̀yin eniyan Jakọbu, iranṣẹ mi,ẹ má sì jẹ́ kí àyà fò yín, ẹ̀yin ọmọ Israẹli.Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.N óo ti òkèèrè wá gbà yín là,N óo gba àwọn ọmọ yín tí wọ́n wà ní ìgbèkùn là pẹlu.Àwọn ọmọ Jakọbu yóo pada ní ìfọ̀kànbalẹ̀ ati ìrọ̀rùn,ẹnikẹ́ni kò sì ní dẹ́rù bà wọ́n mọ́.

11 Nítorí pé mo wà pẹlu yín, n óo gbà yín là.Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé n óo pa gbogbo orílẹ̀-èdè run,gbogbo orílẹ̀-èdè tí mo fọn yín ká sí ni n óo parun patapata,ṣugbọn n kò ní pa ẹ̀yin run.N óo jẹ yín níyà,ṣugbọn n kò ní fi ìyà tí kò tọ́ jẹ yín.Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

12 “Egbò yín kò lè san mọ́,ọgbẹ́ yín sì jinlẹ̀.

13 Kò sí ẹni tí yóo gba ẹjọ́ yín rò,kò ní sí òògùn fún ọgbẹ́ yín,kò ní sí ìwòsàn fun yín.

14 Gbogbo àwọn olólùfẹ́ yín ti gbàgbé yín;wọn kò bìkítà nípa yín mọ́,nítorí mo ti nà yín bí ọ̀tá mi,mo sì fi ìyà jẹ yín bí ọ̀tá tí kò láàánú,nítorí àṣìṣe yín pọ̀,nítorí ẹ̀ṣẹ̀ yín pọ̀ rékọjá ààlà.

15 Kí ló dé tí ẹ̀ ń sunkún,nítorí ìnira yín tí kò lóògùn?Nítorí pé ẹ̀ṣẹ̀ yín pọ̀ rékọjá ààlàni mo ṣe jẹ́ kí àwọn nǹkan wọnyi dé ba yín.

16 Ṣugbọn, gbogbo àwọn tí wọ́n bá jẹ yín run, ni a óo pada jẹ run.Gbogbo àwọn ọ̀tá yín patapata, ni yóo lọ sí ìgbèkùn.Gbogbo àwọn tí wọ́n fogun kó yín ni ogun yóo kó.N óo fi ẹrù àwọn tí wọn ń jà yín lólè fún àwọn akónilẹ́rù.