11 Gòkè lọ sí Gileadi, kí o lọ wá ìwọ̀ra, ẹ̀yin ará Ijipti,asán ni gbogbo òògùn tí ẹ lò,ẹ kò ní rí ìwòsàn.
12 Àwọn orílẹ̀ èdè ti gbọ́ nípa ìtìjú yín,igbe yín ti gba ayé kan;nítorí àwọn ọmọ ogun ń rọ́ lu ara wọn;gbogbo wọn sì ṣubú papọ̀.
13 Ohun tí OLUWA sọ fún wolii Jeremaya nípa Nebukadinesari, ọba Babiloni nígbà tí ó ń bọ̀ wá ṣẹgun ilẹ̀ Ijipti nìyí:
14 Ó ní, “Ẹ kéde ní Ijipti,ẹ polongo ní Migidoli, ní Memfisi ati ní Tapanhesi.Ẹ wí pé, ‘Ẹ gbáradì kí ẹ sì múra sílẹ̀,nítorí ogun yóo run yín yíká.
15 Kí ló dé tí àwọn akọni yín kò lè dúró?Wọn kò lè dúró nítorí péOLUWA ni ó bì wọ́n ṣubú.’
16 Ogunlọ́gọ̀ yín ti fẹsẹ̀ kọ, wọ́n sì ṣubú,wọ́n wá ń wí fún ara wọn pé,‘Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí á pada sọ́dọ̀ àwọn eniyan wa,ati sí ilẹ̀ tí wọn gbé bí wa,nítorí ogun àwọn aninilára.’
17 “Ẹ pa orúkọ Farao, ọba Ijipti dà,ẹ pè é ní, ‘Aláriwo tí máa ń fi anfaani rẹ̀ ṣòfò.’