10 Ohun ìní àwọn ará Kalidea yóo di ìkógun; gbogbo àwọn tí wọn yóo kó wọn lẹ́rù ni yóo kó ẹrù ní àkótẹ́rùn, Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”
11 OLUWA ní, “Ẹ̀yin ará Babiloni, tí ẹ kó àwọn eniyan mi,bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé inú yín dùn ẹ sì ń yọ̀,tí ẹ sì ń ṣe ojúkòkòrò, bí akọ mààlúù tí ń jẹko ninu pápá,tí ẹ sì ń yan bí akọ ẹṣin:
12 Ojú yóo ti olú-ìlú yín lọpọlọpọ,a óo dójú ti ilẹ̀ ìbí yín.Wò ó! Yóo di èrò ẹ̀yìn láàrin àwọn orílẹ̀-èdè,yóo di aṣálẹ̀ tí ó gbẹ.
13 Nítorí ibinu gbígbóná OLUWA,ẹnikẹ́ni kò ní gbé ibẹ̀ mọ́;yóo di ahoro patapata;ẹnu yóo ya gbogbo ẹni tí ó bá gba Babiloni kọjá,wọn yóo sì máa pòṣé nítorí ìyà tí a fi jẹ ẹ́.
14 “Ẹ gbógun ti Babiloni yíká, gbogbo ẹ̀yin tafàtafà. Ẹ máa ta á lọ́fà, ẹ má ṣẹ́ ọfà kankan kù, nítorí pé ó ti ṣẹ OLUWA.
15 Gbogbo ẹ̀yin tí ẹ yí i ká, ẹ hó bò ó, ó ti jọ̀wọ́ ara rẹ̀ sílẹ̀. Àwọn ibi ààbò rẹ̀ ti wó, àwọn odi rẹ̀ sì ti wó lulẹ̀. Nítorí ẹ̀san OLUWA ni, ẹ gbẹ̀san lára rẹ̀; ẹ ṣe sí i bí òun náà ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn.
16 Ẹ pa àwọn afunrugbin run ní Babiloni, ati àwọn tí ń lo dòjé ní ìgbà ìkórè. Olukuluku yóo pada sọ́dọ̀ àwọn eniyan rẹ̀, yóo sì sá pada sí ilẹ̀ rẹ̀, nítorí idà àwọn aninilára.”