Jeremaya 8:10-16 BM

10 Nítorí náà, n óo fi aya wọn fún ẹlòmíràn,n óo fi oko wọn fún àwọn tí yóo ṣẹgun wọn.Nítorí pé láti orí àwọn mẹ̀kúnnù,títí dé orí àwọn eniyan pataki pataki,gbogbo wọn ni wọ́n ń lépa èrè àjẹjù.Láti orí wolii títí kan alufaa, èké ni gbogbo wọn.

11 Wọn kò wẹ egbò àwọn eniyan mi jinná,wọ́n ń kígbe pé, ‘Alaafia ni, alaafia ni,’bẹ́ẹ̀ sì ni kò sí alaafia.

12 Ǹjẹ́ ojú a tilẹ̀ máa tì wọ́nnígbà tí wọ́n bá ń hu ìwà ìbàjẹ́?Rárá o, ojú kì í tì wọ́n,nítorí pé wọn kò lójútì.Nítorí náà àwọn náà óo ṣubúnígbà tí àwọn yòókù bá ṣubú,a óo bì wọ́n ṣubúnígbà tí mo bá ń jẹ wọ́n níyà,OLUWA ló sọ bẹ́ẹ̀.

13 “Ní àkókò ìkórè, kò ní sí èso lórí àjàrà,igi ọ̀pọ̀tọ́ kò ní ní èso lórí,àwọn ewé pàápàá yóo gbẹ,ohun tí mo fún wọn yóo di ti ẹlòmíràn.Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

14 Àwọn eniyan Ọlọrun bá dáhùn pé,“Kí ló dé tí a fi jókòó jẹ̀kẹ̀tẹ̀?Ẹ jẹ́ kí á kó ara wa jọ,kí á sá lọ sí àwọn ìlú olódi,kí á sì parun sibẹ;nítorí OLUWA Ọlọrun wa ti fi wá lé ìparun lọ́wọ́,ó ti fún wa ní omi tí ó ní májèlé mu,nítorí pé a ti ṣẹ̀ ẹ́.

15 À ń retí alaafia,ṣugbọn ire kankan kò dé.Àkókò ìwòsàn ni à ń retí,ṣugbọn ìpayà ni a rí.

16 Ẹ gbọ́ bí ẹṣin wọn tí ń fọn imú, ní ilẹ̀ Dani;gbogbo ilẹ̀ ń mì tìtì nítorí ìró yíyan ẹṣin wọn.Wọ́n wá run ilẹ̀ náà,ati gbogbo ohun tí ó wà ninu rẹ̀,ati ìlú ati àwọn tí wọn ń gbé inú rẹ̀.”