Jeremaya 8:7-13 BM

7 Ẹyẹ àkọ̀ tí ń fò lójú ọ̀run pàápàá mọ àkókò rẹ̀.Bẹ́ẹ̀ sì ni àdàbà, ati lékèélékèé, ati alápàáǹdẹ̀dẹ̀;wọ́n mọ àkókò tí ó yẹ láti ṣípò pada.Ṣugbọn àwọn eniyan mi kò mọ òfin OLUWA.

8 Báwo ni ẹ ṣe lè wí pé,‘Ọlọ́gbọ́n ni wá,a sì mọ òfin OLUWA?’Ṣugbọn àwọn akọ̀wé ti fi gègé irọ́ wọn sọ ọ́ di èké.

9 Ojú yóo ti àwọn ọlọ́gbọ́n:ìdààmú yóo bá wọn,ọwọ́ yóo sì tẹ̀ wọ́n.Wò ó! Wọ́n ti kọ ọ̀rọ̀ OLUWA sílẹ̀,ọgbọ́n wo ni ó kù tí wọ́n gbọ́n?

10 Nítorí náà, n óo fi aya wọn fún ẹlòmíràn,n óo fi oko wọn fún àwọn tí yóo ṣẹgun wọn.Nítorí pé láti orí àwọn mẹ̀kúnnù,títí dé orí àwọn eniyan pataki pataki,gbogbo wọn ni wọ́n ń lépa èrè àjẹjù.Láti orí wolii títí kan alufaa, èké ni gbogbo wọn.

11 Wọn kò wẹ egbò àwọn eniyan mi jinná,wọ́n ń kígbe pé, ‘Alaafia ni, alaafia ni,’bẹ́ẹ̀ sì ni kò sí alaafia.

12 Ǹjẹ́ ojú a tilẹ̀ máa tì wọ́nnígbà tí wọ́n bá ń hu ìwà ìbàjẹ́?Rárá o, ojú kì í tì wọ́n,nítorí pé wọn kò lójútì.Nítorí náà àwọn náà óo ṣubúnígbà tí àwọn yòókù bá ṣubú,a óo bì wọ́n ṣubúnígbà tí mo bá ń jẹ wọ́n níyà,OLUWA ló sọ bẹ́ẹ̀.

13 “Ní àkókò ìkórè, kò ní sí èso lórí àjàrà,igi ọ̀pọ̀tọ́ kò ní ní èso lórí,àwọn ewé pàápàá yóo gbẹ,ohun tí mo fún wọn yóo di ti ẹlòmíràn.Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”