32 Ṣé ọmọbinrin lè gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀?Tabi iyawo àṣẹ̀ṣẹ̀gbé lè gbàgbé àwọn aṣọ rẹ̀?Sibẹ ẹ ti gbàgbé mi tipẹ́.
33 “Ẹ mọ oríṣìíríṣìí ọ̀nà tí eniyan fi í wá olólùfẹ́ kiri,tóbẹ́ẹ̀ tí ẹ ti fi ìrìnkurìn yínkọ́ àwọn obinrin oníwà burúkú.
34 Ẹ̀jẹ̀ àwọn talaka tí kò ṣẹ̀, wà létí aṣọ yín;bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò bá wọn níbi tí wọ́n ti ń fọ́lé.Gbogbo èyí wà bẹ́ẹ̀,
35 sibẹ ẹ̀ ń sọ pé, ‘Ọwọ́ wa mọ́;dájúdájú, OLUWA ti dá ọwọ́ ibinu rẹ̀ dúró lára wa.’Ẹ wò ó! N óo dá yín lẹ́jọ́,nítorí ẹ̀ ń sọ pé ẹ kò dẹ́ṣẹ̀.
36 Ẹ̀ ń fi ara yín wọ́lẹ̀ káàkiri;ẹ̀ ń yà síhìn-ín sọ́hùn-ún!Bí Asiria ti dójú tì yín,bẹ́ẹ̀ ni Ijipti náà yóo dójú tì yín.
37 Ẹ óo ká ọwọ́ lérí ninígbà tí ẹ óo bá jáde níbẹ̀.Nítorí OLUWA ti kọ àwọn tí ẹ gbójúlé,wọn kò sì ní ṣe yín níre.”