1 “Ẹ̀ṣẹ̀ Júdà ni a fi ṣóóṣó irin kọ sílẹ̀èyí tí ó hàn ketekete pẹ̀lú ẹnu ṣóróṣórósí oókan àyà wọn, àti lórí àwọn ìwotó wà lórí pẹpẹ wọn.
2 Kódà àwọn ọmọ wọn rántí pẹpẹàti òpó Áṣérà lẹ́bàá igi tí ó tẹ́ rẹrẹàti àwọn òkè gíga.
3 Àwọn òkè nínú ilẹ̀ àti àwọn ọrọ̀ rẹ̀àti ọlá rẹ̀ ni èmi yóò fi sílẹ̀ bí ìjẹpẹ̀lú àwọn ibi gíga, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ópọ̀ káàkiri orílẹ̀ èdè yín.
4 Láti ipaṣẹ̀ àìṣedéédé yín ni ẹ̀yinyóò ti sọ ogún tí mo fún un yín nù.Èmi yóò fi yín fún ọ̀tá yínbí ẹrú ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò mọ̀; nítoríẹ̀yin ti mú inú bí mi, èyí tí yóò sì wà títí ayé.”