Jeremáyà 41:4-10 BMY

4 Ní ọjọ́ kejì tí wọ́n pa Jedaláyà kí ó tó di wí pé ẹnikẹ́ni mọ̀

5 Àwọn ọgọ́rin ọkùnrin wá láti Ṣékémù, Ṣílò àti Saaríà, wọ́n fa irùngbọ̀n wọn, wọ́n ya aṣọ wọn, wọ́n sá ara wọn lọ́gbẹ́ wọ́n mú ẹbọ ọpẹ́ àti tùràrí wá sí ilé Olúwa.

6 Ísímáẹ́lì ọmọkùnrin Nétanáyà jáde kúrò láti Mísípà láti lọ pàdé wọn. Ó sì ń sunkún bí ó ti ṣe ń lọ, nígbà tí ó pàdé wọn, ó wí pé, “Ẹwá sọ́dọ̀ Jedaláyà ọmọkùnrin Álíkámù.”

7 Nígbà tí wọ́n dé ìlú náà; Ísímáẹ́lì ọmọkùnrin Nètanáyà àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pa wọ́n, wọ́n sì sọ òkú wọn sínú ìhò kan.

8 Ṣùgbọ́n mẹ́wàá nínú wọn sọ fún Ísímáẹ́lì pé, “Má se pa wá! Àwa ní ọkà àti Bálì, òróró àti oyin ní ìpamọ́ nínú oko.” Nítorí náà, ó fi wọ́n sílẹ̀: kò sì pa wọ́n pẹ̀lú àwọn yóòkù.

9 Nísinsìn yìí, ihò náà tí ó kó gbogbo ara àwọn ọkùnrin tí ó ti pa pẹ̀lú Jedaláyà sí ni Ọba Aṣa ń lò gẹ́gẹ́ bí i ààbò nítorí Ọba Báṣì ti Ísírẹ́lì. Ísímáẹ́lì ọmọ Nétanáyà sì ti kó òkú kún inú rẹ̀.

10 Ísímáẹ́lì sì kó gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní Mísípà nígbèkùn, ọmọbìnrin Ọba àti gbogbo àwọn ènìyàn tó kù síbẹ̀ lórí àwọn tí Nebusarádánì balógun àwọn ẹ̀sọ́ ti fi yan Gédáláyà ọmọkùnrin Álíkámù ṣe olórí. Isímáẹ́lì ọmọkùnrin Nétanáyà kó wọn ní ìgbèkùn, ó sì jáde rékọjá sí ọ̀dọ̀ àwọn Ámónì.