13 Ìwọ tí o gbé lẹ́bàá odò púpọ̀,tí o sì ni ọ̀rọ̀ púpọ̀; ìgbẹ̀yìn rẹ ti dé,àní àsìkò láti ké ọ kúrò!
14 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra fún ara rẹ̀,Èmi yóò fún ọ ní ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ eṣú,wọn yóò yọ ayọ̀, iṣẹ́gun lórí rẹ.
15 “Ó dá ilẹ̀ nípa agbára rẹ̀,o dá ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀,o sì tẹ́ ọ̀run pẹ̀lú ìmọ̀ rẹ̀.
16 Nígbà tí ará omi ọ̀run hóó mú kí òfùrufú ru sókè láti ìpẹ̀kun ayé.Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò,ó sì mú afẹ́fẹ́ jáde láti ilé ìṣúra rẹ̀.
17 “Olúkúlùkù ènìyàn ni kò lọ́pọlọtí kò sì ní ìmọ̀, olúkùlúkùalágbẹ̀dẹ ni a kó ìtìjú bá nípa òrìṣà rẹ̀.Àwọn ère rẹ jẹ́ ẹ̀tàn wọn kò ní èémí nínú.
18 Wọn kò já mọ́ nkànkan,wọ́n jẹ́ ohun ẹlẹ́yà nígbà tí ìdájọ́ wọnbá dé, wọn ó ṣègbé.
19 Ẹni tí ó jẹ́ ìpín Jákọ́bù kó rí bí ìwọ̀nyí;nítorí òun ni ó dá ohun gbogbo,àti gbogbo àwọn ẹ̀yà ajogún, Olúwa alágbára ni orúkọ rẹ̀.