17 “Olúkúlùkù ènìyàn ni kò lọ́pọlọtí kò sì ní ìmọ̀, olúkùlúkùalágbẹ̀dẹ ni a kó ìtìjú bá nípa òrìṣà rẹ̀.Àwọn ère rẹ jẹ́ ẹ̀tàn wọn kò ní èémí nínú.
18 Wọn kò já mọ́ nkànkan,wọ́n jẹ́ ohun ẹlẹ́yà nígbà tí ìdájọ́ wọnbá dé, wọn ó ṣègbé.
19 Ẹni tí ó jẹ́ ìpín Jákọ́bù kó rí bí ìwọ̀nyí;nítorí òun ni ó dá ohun gbogbo,àti gbogbo àwọn ẹ̀yà ajogún, Olúwa alágbára ni orúkọ rẹ̀.
20 “Ìwọ ni kùmọ̀ ohun èlò ogun mi,ohun èlò ìjà mi, pẹ̀lú rẹ èmi ó fọ́ orílẹ̀ èdè túútúú,èmi ó bà àwọn ilé Ọba jẹ́.
21 Pẹ̀lú rẹ, èmi ó pa ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún pẹ̀lú rẹ̀;èmi ó ba kẹ̀kẹ́ ogun jẹ́ pẹ̀lúèmi ó pa awakọ̀
22 Pẹ̀lú rẹ, mo pa ọkùnrin àti obìnrin,pẹ̀lú rẹ, mo paàgbàlagbà àti ọmọdé,Pẹ̀lú rẹ, mo pa ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin.
23 Pẹ̀lú rẹ, mo pa olùsọ́ àgùntànàti agbo àgùntàn rẹ̀;pẹ̀lú rẹ, mo pa àgbẹ̀ àti màlúù,Pẹ̀lú rẹ, mo pa gómìnà àti àwọn alákòóṣo ìjọba rẹ̀.