24 Àwa ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn,ọwọ́ wa sì di rírọ, ìrora sì mú wabí ìrora bí obìnrin tí í rọbí.
25 Má ṣe jáde lọ sí orí i pápátàbí kí o máa rìn ní àwọnojú ọ̀nà, nítorí ọ̀tá náà ní idà,ìpayà sì wà níbi gbogbo.
26 Ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ gbé asọ ọ̀fọ̀wọ̀, kí ẹ sì sùn nínú eérú, ẹsọ̀fọ̀ pẹ̀lú ìpohùnréré ẹkúngẹ́gẹ́ bí i lórí ọmọkùnrin yín, kanṣoṣonítorí pé lójijì ni àwọn apanirun yóò kọlù wá.
27 “Èmi ti fi ẹ́ ṣe ẹni tí yóò máa yọ́irú àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bi irintútù, kí wọn kí ó lè ṣe àkíyèsí,kí ó sì dán ọ̀nà wọn wò.
28 Ọlọ́tẹ̀ tí ọkàn rẹ̀ le ní gbogbo wọn. Wọ́n ńlọ káàkiri láti sọ̀rọ̀ òdì. Wọ́n jẹ́ idẹ àti irin,wọ́n sì kún fún ìwà ìbàjẹ́.
29 Ewìrì a fẹ́ná kíkankíkán,kí ó lè yọ́ òjé,ẹni tí ń yọ́ ọ ń yọ́ ọ lásán;a ko si ya ènìyàn búburú kúrò.
30 A pè wọ́n ní fàdákà tí a kọ̀ sílẹ̀,nítorí Olúwa ti kọ̀ wọ́n sílẹ̀.”