17 “Wò ó, èmi yóò rán àwọn ejò olóró síàárin yín, paramọ́lẹ̀ tí ẹ kò lè pa orówọn, yóò sì bù yín jẹ,”ni Olúwa wí.
18 Olùtùnú mi, nígbà tí ìbànújẹ́ ọkàn mirẹ̀wẹ̀sì nínú mi.
19 Fetí sí igbe àwọn ènìyàn mi láti ilẹ̀ tó jìn:“Olúwa kò ha sí ní Síóní bí?Ọba rẹ̀ kò sí níbẹ̀ mọ́ ni?”“È é ṣe tí wọ́n fi mú mi bínú pẹ̀lú ère wọn, pẹ̀lú àwọnòrìṣà àjòjì tí wọn kò ní láárí?”
20 “Ìkóórè ti ré kọ́ja, ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn ti paríṣíbẹ̀, a kò gbà wá là.”
21 Níwọ̀n ìgbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run,èmi náà run pẹ̀lú, mo sọ̀fọ, ìrora sì mú mi káká.