17 Ojú mi wà ní gbogbo ọ̀nà wọn, wọn kò pamọ́ fún mi bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀ṣẹ̀ wọn kò farasin lójú mi.
18 Èmi yóò san ẹ̀san ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn fún wọn ní ìlọ́poméjì, nítorí wọ́n ti ba ilẹ̀ mi jẹ́ pẹ̀lú àwọn ère wọn aláìlẹ́mìí, wọ́n sì ti kún ohun ìní mi pẹ̀lú ẹ̀gbin òrìṣà wọn.”
19 Olúwa, alágbára àti okun miẹni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njúÁà! àwọn orílẹ̀ èdè yóò wá látiòpin ayé wí pé,“Àwọn baba ńlá wa kò ní ohunkan bí kò ṣe ẹ̀gbin òrìsà,ìríra tí kò dára fún wọn nínú rẹ̀.
20 Ṣé àwọn ènìyàn lè dá Ọlọ́runfún ara wọn bí? Bẹ́ẹ̀ ni,ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí kì í ṣe Ọlọ́run.”