1 Ọ̀rọ̀ náà sì tọ Jeremáyà wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa lẹ́yìn tí Nebukadinésárì balógun àwọn ẹ̀ṣọ́ ti tú u sílẹ̀ ní Rámà. Ó rí Jeremáyà tí a fi ẹ̀wọ̀n dè láàrin gbogbo àwọn tí wọ́n mú ní Jérúsálẹ́mù àti Júdà. Wọ́n kó lọ sí ilẹ̀ àjèjì Bábílónì.
2 Nígbà tí balógun ẹ̀ṣọ́ rí Jeremáyà, ó sọ fún-un wí pé, “Olúwa Ọlọ́run rẹ ni ó pàṣẹ ibí yìí fún mi.
3 Nísinsìn yìí, Olúwa ti mú un jáde; ó ti ṣe gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ pé òun yóò ṣe. Gbogbo èyí ṣẹlẹ̀ nítorí wí pé ẹ̀yin ènìyàn ṣẹ̀ sí Olúwa, àti pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀.
4 Ṣùgbọ́n, ní òní yìí mò ń tú ọ sílẹ̀ kúrò nínú ẹ̀wọ̀n tí ó wà ní ọwọ́ rẹ. Bí o bá fẹ́, tẹ̀lémi kálọ sí Bábílónì, èmi yóò sì bojútó ọ; ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá fẹ́, má ṣe wá. Wò ó, gbogbo orílẹ̀ èdè wà níwájú rẹ, lọ sí ibikíbi tí ó bá tẹ́ ọ lọ́rùn.”