3 Wọ́n ti pèsè ahọ́n wọn sílẹ̀ bí ọfàláti fi pa irọ́; kì í ṣe nípa òótọ́ni wọ́n fi borí ní ilẹ̀ náà. Wọ́n ńlọ láti inú ẹ̀ṣẹ̀ kan sí òmíràn,wọn kò sì náání mi,ní Olúwa wí.
4 Ṣọ́ra fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ; má ṣegbẹ́kẹ̀lé àwọn arákùnrin rẹnítorí pé oníkálukú arákùnrinjẹ́ atannijẹ, oníkálukú ọ̀rẹ́ sì jẹ́ abanijẹ́.
5 Ọ̀rẹ́ ń dalẹ̀ ọ̀rẹ́. Kò sì sí ẹnitó sọ òótọ́, wọ́n ti kọ́ ahọ́n wọnláti máa purọ́. Wọ́n sọ ara wọndi onírẹ̀wẹ̀sì pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀
6 Ó ń gbé ní àárin ẹ̀tànwọ́n kọ̀ láti mọ̀ mí nínúẹ̀tàn wọn,ni Olúwa wí.
7 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ ogun wí:“Wò ó, èmi dán wọn wo; nítorí pékí ni èmi tún le è ṣe? Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi?
8 Ahọ́n wọn dàbí ọfà olóróó ń sọ ẹ̀tàn; oníkálukú sì ńfi ẹnu rẹ̀ sọ̀rọ̀ àlàáfíà síaládúgbò rẹ̀; ní inúọkàn rẹ̀, ó dẹ tàkúté sílẹ̀.
9 Èmi kì yóò háa fi ìyà jẹ wọ́n nítorí èyí?”ni Olúwa wí.“Èmi kì yóò ha gbẹ̀san arami lórí irú orílẹ̀ èdè yìí bí?”