27 Nwọn kì yio si dubulẹ tì awọn alagbara ti o ṣubu ninu awọn alaikọlà, ti nwọn sọkalẹ lọ si ipò-okú pẹlu ihámọra ogun wọn: nwọn ti fi idà wọn rọ ori wọn, ṣugbọn aiṣedẽde wọn yio wà lori egungun wọn, bi nwọn tilẹ jẹ ẹ̀ru awọn alagbara ni ilẹ alãye.
28 Lõtọ, a o fọ́ ọ lãrin awọn alaikọlà, iwọ o si dubulẹ tì awọn ti a fi idà pa.
29 Edomu wà nibẹ, awọn ọba rẹ̀, ati awọn ọmọ-alade rẹ̀, ti a tẹ́ pẹlu agbara wọn tì awọn ti a fi idà pa, nwọn o dubulẹ tì awọn alaikọlà, ati pẹlu awọn ti o sọkalẹ lọ si ihò.
30 Awọn ọmọ-alade ariwa wà nibẹ, gbogbo wọn, ati awọn ara Sidoni, ti nwọn sọkalẹ lọ pẹlu awọn ti a pa; pẹlu ẹ̀ru wọn, oju agbara wọn tì wọn; nwọn si dubulẹ li alaikọlà pẹlu awọn ti a fi idà pa, nwọn si rù itiju wọn pẹlu awọn ti o sọkalẹ lọ si ihò.
31 Farao yio ri wọn, a o si tù u ninu lori gbogbo ọ̀pọlọpọ enia rẹ̀, ani Farao ati gbogbo ogun rẹ̀ ti a fi idà pa, li Oluwa Ọlọrun wi.
32 Nitoriti emi ti dá ẹ̀ru mi silẹ ni ilẹ alãye: a o si tẹ́ ẹ si ãrin awọn alaikọlà, pẹlu awọn ti a fi idà pa ani Farao ati gbogbo ọ̀pọlọpọ enia rẹ̀, li Oluwa Ọlọrun wi.