26 Emi o tì ọ sode, ati iya rẹ ti o bi ọ si ilẹ miran, nibiti a kò bi nyin si; nibẹ li ẹnyin o si kú.
27 Ṣugbọn ilẹ na ti ẹnyin fẹ li ọkàn nyin lati pada si, nibẹ ni ẹnyin kì o pada si mọ.
28 Ọkunrin yi, Koniah, ohun-èlo ẹlẹgan, fifọ ha ni bi? o ha dabi ohun-èlo ti kò ni ẹwà lara? ẽṣe ti a tì wọn jade, on, ati iru-ọmọ rẹ̀, ti a si le wọn jade si ilẹ ti nwọn kò mọ̀?
29 Ilẹ! ilẹ! ilẹ! gbọ́ ọ̀rọ Oluwa!
30 Bayi li Oluwa wi, Ẹ kọwe pe, ọkunrin yi alailọmọ ni, ẹniti kì yio ri rere li ọjọ aiye rẹ̀: nitori ọkan ninu iru-ọmọ rẹ̀ kì yio ri rere, ti yio fi joko lori itẹ Dafidi, ti yio si fi tun jọba lori Juda.