21 Ati nigbati Jehoiakimu, ọba, pẹlu gbogbo ọkunrin alagbara rẹ̀, ati awọn ijoye gbọ́ ọ̀rọ rẹ̀, ọba nwá a lati pa; ṣugbọn nigbati Urijah gbọ́, o bẹ̀ru, o salọ o si wá si Egipti.
22 Jehoiakimu, ọba, si rán enia lọ si Egipti, ani Elnatani, ọmọ Akbori ati enia miran pẹlu rẹ̀ lọ si Egipti.
23 Nwọn si mu Urijah lati Egipti tọ Jehoiakimu ọba wá; ẹni ti o fi idà pa a, o si sọ okú rẹ̀ sinu isa-okú awọn enia lasan.
24 Bẹ̃ni ọwọ Ahikamu, ọmọ Safani mbẹ pẹlu Jeremiah, ki nwọn ki o má ba fi i le awọn enia lọwọ lati pa.