5 Emi o tọ̀ awọn ẹni-nla lọ, emi o si ba wọn sọrọ; nitori nwọn ti mọ̀ ọ̀na Oluwa, idajọ Ọlọrun wọn. Ṣugbọn awọn wọnyi ti jumọ ṣẹ́ àjaga, nwọn si ti ja ìde.
6 Nitorina kiniun lati inu igbo wa yio pa wọn, ikõko aṣálẹ̀ yio pa wọn run, ẹkùn yio mã ṣọ ilu wọn: ẹnikẹni ti o ba ti ibẹ jade li a o ya pẹrẹpẹrẹ: nitori ẹ̀ṣẹ wọn pọ̀, ati ipẹhinda wọn le.
7 Emi o ha ṣe dari eyi ji ọ? awọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mi silẹ, nwọn si fi eyi ti kì iṣe ọlọrun bura: emi ti mu wọn bura, ṣugbọn nwọn ṣe panṣaga, nwọn si kó ara wọn jọ si ile àgbere.
8 Nwọn jẹ akọ ẹṣin ti a bọ́ rere ti nrin kiri, olukuluku nwọn nyán si aya aladugbo rẹ̀.
9 Emi kì yio ha ṣe ibẹwo nitori nkan wọnyi? li Oluwa wi, ẹmi mi kì yio ha gbẹsan lara iru orilẹ-ède bi eyi?
10 Ẹ goke lọ si ori odi rẹ̀, ki ẹ si parun; ṣugbọn ẹ máṣe pa a run tan: ẹ wó kùrùkúrù rẹ̀ kuro nitori nwọn kì iṣe ti Oluwa.
11 Nitori ile Israeli ati ile Juda ti huwa arekereke gidigidi si mi, li Oluwa wi.