1 “Lọ sókè àti sódò àwọn òpó Jérúsálẹ́mùWò yíká, kí o sì mọ̀,kí o sì wá kiriBí o bá le è rí ẹnìkan,tí ó jẹ́ olóòótọ́ àti olódodo,N ó dárí jìn ìlú yìí.
2 Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’síbẹ̀ wọ́n búra èké.”
3 Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n.Ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà.Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ,wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.
4 Èmi sì rò pé, “talákà ni àwọn yìíwọn kò lóyenítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa,àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.