6 Emi o si kọju mi si wọn fun rere, emi o si mu wọn pada wá si ilẹ yi, emi o gbe wọn ró li aitun wó wọn lulẹ, emi o gbìn wọn, li aitun fà wọn tu.
7 Emi o si fun wọn li ọkàn lati mọ̀ mi, pe, Emi li Oluwa, nwọn o si jẹ enia mi, emi o si jẹ Ọlọrun wọn, nitoripe nwọn o fi gbogbo ọkàn wọn yipada si mi.
8 Ati gẹgẹ bi eso-ọ̀pọtọ biburujù ti a kò le jẹ, nitoriti nwọn burujù, bayi li Oluwa wi, Bẹ̃ gẹgẹ ni emi o ṣe Sedekiah, ọba Juda, ati awọn ijoye rẹ̀, ati awọn ti o kù ni Jerusalemu, ati awọn iyokù ni ilẹ yi ati awọn ti ngbe ilẹ Egipti.
9 Emi o fi wọn fun iwọsi ati fun ibi ninu gbogbo ijọba aiye, lati di ìtiju, owe, ẹsin, ati ẹ̀gan ni ibi gbogbo, ti emi o le wọn si.
10 Emi o si rán idà, ìyan, ati ajakalẹ-arun, si ãrin wọn, titi nwọn o fi parun kuro ni ilẹ eyi ti emi fi fun wọn ati fun awọn baba wọn.