Aisaya 10:11-17 BM

11 ṣé n kò ní lè ṣe sí Jerusalẹmu ati àwọn oriṣa rẹ̀bí mo ti ṣe Samaria ati àwọn oriṣa rẹ̀?”

12 Nígbà tí OLUWA bá parí bírà tí ó ń dá ní òkè Sioni ati ní Jerusalẹmu,yóo fìyà jẹ ọba Asiria fún ìwà ìgbéraga ati àṣejù rẹ̀.

13 Nítorí ó ní,“Agbára mi ni mo fi ṣe èyí,ọgbọ́n mi ni mo fi ṣe énítorí pé mo jẹ́ amòye.Mo yí ààlà àwọn orílẹ̀-èdè pada,mo kó ẹrù tí ó wà ninu ilé ìṣúra wọn.Mo ré àwọn tí wọ́n jókòó lórí ìtẹ́ bọ́ sílẹ̀ bí alágbára ọkunrin.

14 Mo nawọ́ kó ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè,bí ẹni nawọ́ kó ọmọ ẹyẹ.Mo kó gbogbo ayé,bí ẹni kó ẹyin ẹyẹ tí ó kọ ẹyin rẹ̀ sílẹ̀, tí ó fò lọ,kò sí ẹnìkan tí ó lè ṣe nǹkankan,kò sí ẹnìkan tí ó lanu sọ̀rọ̀,bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kò gbin.”

15 Ǹjẹ́ fáàrí àáké lè pọ̀ ju ti ẹni tí ó ń fi gégi lọ?Tabi ayùn lè fọ́nnu sí ẹni tí ó ń fi rẹ́ igi?Ǹjẹ́ kùmọ̀ lè mú ẹni tí ó ń lò ó lọ́wọ́,tabi kí ọ̀pá mú ẹni tí ó ni í lọ́wọ́?

16 Nítorí náà, OLUWA àwọn ọmọ ogun yóo rán àìsàn apanirunsí ààrin àwọn akọni ọmọ ogun rẹ̀.Dípò ohun tí wọ́n fi ń ṣe ògo,ajónirun yóo jó wọn bí ìgbà tí iná bá jóni.

17 Ìmọ́lẹ̀ Israẹli yóo di iná,Ẹni Mímọ́ rẹ̀ yóo di ahọ́n iná;yóo sì jó àwọn ẹ̀gún wẹ́wẹ́ ati ẹ̀gún ọ̀gàn rẹ̀ run ní ọjọ́ kan.