10 Wọ́n ti kó ayọ̀ ati ìdùnnú lọ kúrò ninu oko eléso;ẹnikẹ́ni kò kọrin bẹ́ẹ̀ ni kò sí ariwo híhó ninu ọgbà àjàrà wọn.Kò sí àwọn tí ó ń pọn ọtí ninu rẹ̀ mọ́bẹ́ẹ̀ ni a kò gbọ́ ariwo àwọn tí ń pọn ọtí mọ́.
11 Nítorí náà, ẹ̀mí mi kọrin arò bíi ti dùùrù fún Moabu,ọkàn mi kérora, fún Moabu ati Kiri Heresi.
12 Nígbà tí Moabu bá wá siwaju,tí ó fi gbogbo agbára gbadura ninu ilé oriṣa rẹ̀,títí ó fi rẹ̀ ẹ́,adura rẹ̀ kò ní gbà.
13 Ọ̀rọ̀ tí OLUWA ti kọ́ sọ nípa Moabu tẹ́lẹ̀ nìyí.
14 Ṣugbọn nisinsinyii, OLUWA ní, “Nígbà tí a óo fi rí ọdún mẹta, tíí ṣe iye ọdún alágbàṣe, a óo ti sọ ògo Moabu di ilẹ̀. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé eniyan inú rẹ̀ pọ̀, àwọn díẹ̀ ni yóo ṣẹ́kù, àárẹ̀ yóo sì ti mú wọn.”