Aisaya 16:3-9 BM

3 “Gbà wá ní ìmọ̀ràn,máa ṣe ẹ̀tọ́ fún wa.Fi òjìji rẹ dáàbò bò wá,kí ara lè tù wá lọ́sàn-án gangan,bí ẹni pé alẹ́ ni.Dáàbò bo àwọn tí a lé jáde;má tú àṣírí ẹni tí ń sálọ.

4 Jẹ́ kí àwọn tí a lé jáde ní Moabu, máa gbé ààrin yín.Dáàbò bò wọ́n lọ́wọ́ àwọn apanirun.”Nígbà tí aninilára kò bá sí mọ́ tí ìparun bá dópin,tí atẹnimọ́lẹ̀ bá ti kúrò ní ilẹ̀ náà.

5 Nígbà náà a óo fìdí ìtẹ́ múlẹ̀ pẹlu ìfẹ́ tí kì í yẹ̀.Ẹnìkan tí ń ṣe ìdájọ́ ẹ̀tọ́ ati òdodo yóo jókòó lórí ìtẹ́ náà,Yóo dúró lórí òtítọ́ ní ìdílé Dafidi.

6 A ti gbọ́ ìròyìn ìgbéraga Moabu,bí ó ṣe ń ṣe àfojúdi tí ó sì ń sọ ìsọkúsọ:ṣugbọn lásán ni ìgbéraga rẹ̀.

7 Nítorí náà, kí Moabu máa pohùnréré ẹkún,kí gbogbo eniyan máa sun ẹkún arò ní Moabu.Wọn óo sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn,nígbà tí wọn ba ranti àkàrà Kiri Heresi,tí ó ní èso àjàrà ninu.

8 Gbogbo oko ni ó rọ ní Heṣiboni;bẹ́ẹ̀ náà ni ọgbà Sibuma:àwọn olórí orílẹ̀-èdè ti gé àwọn ẹ̀ka rẹ̀ lulẹ̀,èyí tí ó tàn kálẹ̀ dé Jaseri títí dé inú aṣálẹ̀.Ìtàkùn rẹ̀ tàn kálẹ̀,wọ́n kọjá sí òdìkejì òkun.

9 Nítorí náà mo sọkún fún ọgbà àjàrà Sibumabí mo ṣe sọkún fún Jaseri;mo sì sọkún nítorí Heṣiboni ati Eleale,mo sọkún, omi ń dà lójú mi pòròpòrònítorí gbogbo ìkórè yín, ati èso oko yín ni ogun ti kó lọ.