14 Ẹ bu omi wá fún ẹni tí òùngbẹ ń gbẹ.Ẹ gbé oúnjẹ pàdé ẹni tí ń sá fógun, ẹ̀yin ará ilẹ̀ Tema.
15 Wọ́n ń sá fún idà,wọ́n sá fún idà lójú ogun.Wọ́n ń sá fún àwọn tafàtafà,wọ́n sá fún líle ogun.
16 OLUWA sọ fún mi pé, “Kí ó tó tó ọdún kan, ní ìwọ̀n ọdún alágbàṣe kan, gbogbo ògo Kedari yóo dópin;
17 díẹ̀ ni yóo sì kù ninu àwọn tafàtafà alágbára ọmọ Kedari; nítorí OLUWA Ọlọrun Israẹli ló sọ bẹ́ẹ̀.”