4 Nítorí náà, ni mo ṣe sọ pé,“Ẹ ṣíjú kúrò lára miẹ jẹ́ kí n sọkún, kí n dami lójú pòròpòrò,ẹ má ṣòpò pé ẹ óo rẹ̀ mí lẹ́kún,nítorí ìparun àwọn ará Jerusalẹmu, àwọn eniyan mi.”
5 Nítorí OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun ti ya ọjọ́ kan sọ́tọ̀,ọjọ́ ìrúkèrúdò ati ìdágìrì ati ìdàrúdàpọ̀, ní àfonífojì ìran.Ọjọ́ wíwó odi ìlú palẹ̀ati igbe kíké láàrin àwọn òkè ńlá.
6 Àwọn ọmọ ogun Elamu gbé ọfà wọn kọ́ èjìká,pẹlu kẹ̀kẹ́-ogun ati àwọn ẹlẹ́ṣin,àwọn ọmọ ogun Kiri sì tọ́jú asà wọn.
7 Àwọn àfonífojì dáradára yín kún fún kẹ̀kẹ́-ogunàwọn ẹlẹ́ṣin sì dúró sí ipò wọn lẹ́nu ibodè;
8 ó ti tú aṣọ lára Juda.Ní ọjọ́ náà, ẹ gbẹ́kẹ̀lé àwọn ohun ìjà tí ó wà ninu Ilé-Igbó,
9 ẹ rí i pé ibi tí ògiri ìlú Dafidi ti sán pọ̀, ẹ sì gbá omi inú adágún tí ó wà ní ìsàlẹ̀ jọ.
10 Ẹ ka iye ilé tí ó wà ní Jerusalẹmu, ẹ sì wó àwọn kan palẹ̀ ninu wọn, kí ẹ lè rí òkúta tún odi ìlú ṣe.