7 Àwọn àfonífojì dáradára yín kún fún kẹ̀kẹ́-ogunàwọn ẹlẹ́ṣin sì dúró sí ipò wọn lẹ́nu ibodè;
8 ó ti tú aṣọ lára Juda.Ní ọjọ́ náà, ẹ gbẹ́kẹ̀lé àwọn ohun ìjà tí ó wà ninu Ilé-Igbó,
9 ẹ rí i pé ibi tí ògiri ìlú Dafidi ti sán pọ̀, ẹ sì gbá omi inú adágún tí ó wà ní ìsàlẹ̀ jọ.
10 Ẹ ka iye ilé tí ó wà ní Jerusalẹmu, ẹ sì wó àwọn kan palẹ̀ ninu wọn, kí ẹ lè rí òkúta tún odi ìlú ṣe.
11 Ẹ wa kòtò sí ààrin ògiri mejeeji, Kí ẹ lè rí ààyè fa omi inú odò àtijọ́ sí. Ṣugbọn ẹ kò wo ojú ẹni tí ó ṣe ohun tí ń ṣẹlẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò bìkítà fún ẹni tí ó ṣètò rẹ̀ láti ìgbà pípẹ́ wá.
12 Ní ọjọ́ náà,OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun fi ìpè sóde pé,kí ẹ máa sọkún, kí ẹ máa ṣọ̀fọ̀,kí ẹ fá orí yín, kí ẹ sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ bora.
13 Ṣugbọn dípò kí ẹ ṣe bẹ́ẹ̀,ẹ̀ ń yọ̀, inú yín ń dùn.Ẹ̀ ń pa mààlúù, ẹ̀ ń pa aguntan,ẹ̀ ń jẹ ẹran, ẹ̀ ń mu ọtí waini.Ẹ̀ ń wí pé, “Ẹ jẹ́ kí á jẹ, kí á mu!Nítorí pé lọ́la ni a óo kú.”