1 Ní àkókò náà,orin tí wọn óo máa kọ ní ilẹ̀ Juda ni pé:“A ní ìlú tí ó lágbára,ó fi ìgbàlà ṣe odi ati ibi ààbò.
2 Ẹ ṣí ìlẹ̀kùn ibodè,kí orílẹ̀-èdè olódodo, tí ń ṣe òtítọ́ lè wọlé.
3 O óo pa àwọn tí wọ́n gbé ọkàn wọn lé ọ mọ́ ní alaafia pípé,nítorí pé wọ́n gbẹ́kẹ̀lé ọ.
4 Gbẹ́kẹ̀lé OLUWA títí lae,nítorí àpáta ayérayé ni OLUWA Ọlọrun.