6 Wọ́n ń tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀,bí àwọn òtòṣì tí ń tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀bẹ́ẹ̀ ni àwọn aláìní ń tẹ̀ ẹ́.”
7 Ọ̀nà títẹ́jú ni ọ̀nà àwọn olódodoó mú kí ọ̀nà àwọn olódodo máa dán.
8 Àwa dúró dè ọ́ ní ọ̀nà ìdájọ́ rẹ, OLUWA,orúkọ rẹ ati ìrántí rẹ ni ọkàn wa ń fẹ́.
9 Ọkàn mi ń ṣe àfẹ́rí rẹ lálẹ́,mo sì ń fi tọkàntọkàn wá ọnítorí nígbà tí ìlànà rẹ bá wà láyéni àwọn ọmọ aráyé yóo kọ́ òdodo.
10 Bí a bá ṣàánú ẹni ibi,kò ní kọ́ láti ṣe rere.Yóo máa ṣe ibi ní ilẹ̀ àwọn olódodo,kò sì ní rí ọlá ńlá OLUWA.
11 OLUWA o ti gbé ọwọ́ rẹ sókè láti jẹ àwọn ọ̀tá níyà,ṣugbọn wọn kò rí i.Jẹ́ kí wọn rí i péọ̀rọ̀ àwọn eniyan rẹ jẹ ọ́ lógún,kí ojú sì tì wọ́n.Jẹ́ kí iná tí o dá fún àwọn ọ̀tá rẹ jó wọn run.
12 OLUWA ìwọ yóo fún wa ní alaafia,nítorí pé ìwọ ni o ṣe gbogbo iṣẹ́ wa fún wa.