4 Inú kò bí mi,ǹ bá rí ẹ̀gún ati pàǹtí ninu rẹ̀,ǹ bá gbógun tì wọ́n,ǹ bá jó gbogbo wọn níná papọ̀.
5 Ṣugbọn bí wọn bá fi mí ṣe ààbò,kí wọn wá kí á parí ìjà láàrin ara wa;kí wọn wá kí á parí ìjà láàrin ara wa.”
6 Ní ọjọ́ iwájúJakọbu yóo ta gbòǹgbò,Israẹli yóo tanná, yóo rúwé,yóo so, èso rẹ̀ yóo sì kún gbogbo ayé.
7 Ṣé OLUWA ti jẹ wọ́n níyà bí ó ti fìyà jẹ àwọn tí ó jẹ wọ́n níyà?Ṣé ó ti pa wọ́n bí ó ti pa àwọn tí ó pa wọ́n?
8 OLUWA fìyà jẹ àwọn eniyan rẹ̀,ó kó wọn lọ sí ìgbèkùn;ó lé wọn jáde ní ìlú,bí ìgbà tí ẹ̀fúùfù líle bá ń fẹ́ láti ìlà oòrùn.
9 Ọ̀nà tí a fi lè pa ẹ̀ṣẹ̀ Jakọbu rẹ́,tí a fi lè mú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ kúrò ni pé:Kí ó fọ́ gbogbo òkúta àwọn pẹpẹ oriṣa rẹ̀ túútúú,bí ẹfun tí a lọ̀ kúnná;kí ó má ku ère oriṣa Aṣera tabi pẹpẹ turari kan lóòró.
10 Nítorí ìlú olódi ti di ahoro,ó di ibùgbé tí a kọ̀ sílẹ̀, tí a sì patì bí aginjù;ibẹ̀ ni àwọn ọmọ mààlúù yóo ti máa jẹko,wọn óo dùbúlẹ̀ níbẹ̀, wọn óo sì máa jẹ àwọn ẹ̀ka igi rẹ̀.