6 Àsọtẹ́lẹ̀ nípa àwọn ẹranko ilẹ̀ Nẹgẹbu nìyí:“Wọ́n di àwọn nǹkan ìní wọn sí ẹ̀yìn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,wọ́n sì di ìṣúra wọn sí ẹ̀yìn ràkúnmí.Wọ́n ń la ilẹ̀ ìṣòro ati wahala kọjá.Ilẹ̀ àwọn akọ kinniun ati abo kinniun,ilẹ̀ paramọ́lẹ̀ ati ejò amúbíiná tí ń fò.Wọ́n ń lọ sọ́dọ̀ àwọn eniyan tí kò lè ṣe wọ́n ní anfaani.
7 Nítorí ìmúlẹ̀mófo ni ìrànwọ́ Ijipti.Nítorí náà ni mo ṣe pè é ní,‘Rahabu tí ń jókòó lásán.’ ”
8 Nisinsinyii lọ kọ ọ́ sílẹ̀ níwájú wọn,kí o sì kọ ọ́ sinu ìwé,kí ó lè wà títí di ẹ̀yìn ọ̀la,gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí títí lae;
9 nítorí aláìgbọràn eniyan ni wọ́n,Òpùrọ́ ọmọ tí kìí fẹ́ gbọ́ ìtọ́ni OLUWA.
10 Wọ́n á máa sọ fún àwọn aríran pé,“Ẹ má ríran mọ.”Wọ́n á sì máa sọ fún àwọn wolii pé,“Ẹ má sọ àsọtẹ́lẹ̀ òtítọ́ fún wa mọ́,ọ̀rọ̀ dídùn ni kí ẹ máa sọ fún wa,kí ẹ sì máa sọ àsọtẹ́lẹ̀ ẹ̀tàn fún wa.
11 Ẹ fi ojú ọ̀nà sílẹ̀, ẹ yà kúrò lójú ọ̀nà,ẹ má sọ nípa Ẹni Mímọ́ Israẹli fún wa mọ́.”
12 Nítorí náà, Ẹni Mímọ́ Israẹli ní:“Nítorí pé ẹ kẹ́gàn ọ̀rọ̀ yìí,ẹ gbẹ́kẹ̀lé ìninilára ati ẹ̀tàn,ẹ sì gbára lé wọn,