13 Mo kígbe fún ìrànlọ́wọ́ títí ilẹ̀ fi mọ́ó fọ́ gbogbo egungun mi bí kinniun ti máa ń fọ́ egungun.Tọ̀sán-tòru mo rò pé Ọlọrun ń fi òpin sí ayé mi ni.
14 Ọkàn mi ń ṣe hílàhílo bí ẹyẹ aláàpáǹdẹ̀dẹ̀ ati ẹyẹ àkọ̀,mò ń ké igbe arò bí àdàbà.Mo wòkè títí ojú ń ro mí,ara ń ní mí, OLUWA, nítorí náà ṣe ààbò mi.
15 Ṣugbọn kí ni mo lè sọ?Nítorí pé ó ti bá mi sọ̀rọ̀,òun fúnrarẹ̀ ni ó sì ṣe éOorun kò kùn mí nítorí pé ọkàn mi bàjẹ́.
16 OLUWA, nǹkan wọnyi ni ó mú eniyan wà láàyè,ninu gbogbo rẹ̀ èmi náà yóo wà láàyè.Áà, jọ̀wọ́ wò mí sàn, kí o mú mi wà láàyè.
17 Nítorí ìlera mi ni mo ṣe ní ìbànújẹ́ lọpọlọpọ;ìwọ ni o dì mí mú,tí n kò fi jìn sinu kòtò ìparun,nítorí o ti sọ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi di ohun ìgbàgbé.
18 Ibojì kò lè dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ,bẹ́ẹ̀ ni ikú kò lè yìn ọ́;kò sí ìrètí mọ́ fún àwọn tí wọ́n ti lọ sinu isà òkú,wọn kò lè gbẹ́kẹ̀lé òdodo rẹ mọ́.
19 Alààyè, àní alààyè, ni ó lè máa yìn ọ́bí mo ti yìn ọ́ lónìí.Baba a máa kọ́ àwọn ọmọ rẹ̀, nípa òdodo rẹ.