8 “Èmi ni OLUWA, bẹ́ẹ̀ ni orúkọ mi;n kò ní fi ògo mi fún ẹlòmíràn,n kò sì ní fi ìyìn mi fún ère.
9 Wò ó! Àwọn nǹkan àtijọ́ ti kọjá,àwọn nǹkan tuntun ni mò ń kéde nisinsinyii.Kí wọn tó yọjú jáde rárá,ni mo ti sọ fún ọ nípa wọn.”
10 Ẹ kọ orin tuntun sí OLUWA;ẹ kọ orin ìyìn rẹ̀ láti òpin ayé.Ẹ̀yin èrò inú ọkọ̀ lójú agbami òkun,ati gbogbo ohun tí ó wà ninu omi òkun;ati àwọn erékùṣù ati àwọn tí ń gbé inú wọn.
11 Kí aṣálẹ̀ ati àwọn ìlú inú rẹ̀ kọ orin ìyìn sókè,ati àwọn abúlé agbègbè Kedari;kí àwọn ará ìlú Sela kọrin ayọ̀,kí wọn máa kọrin lórí àwọn òkè.
12 Kí wọn fi ògo fún OLUWA,kí wọn kéde ìyìn rẹ̀ ní àwọn erékùṣù.
13 OLUWA yọ jáde lọ bí alágbára ọkunrin,ó ru ibinu rẹ̀ sókè bí ọkunrin ogun,ó kígbe, ó sì bú ramúramù.Ó fihàn pé alágbára ni òun níwájú àwọn ọ̀tá rẹ̀.OLUWA ní:
14 “Ó ti pẹ́ tí mo ti dákẹ́ jẹ́ẹ́,mo dákẹ́ jẹ́ẹ́, mo mára dúró.Ṣugbọn nisinsinyii, n óo kígbe,bí obinrin tí ń rọbí lọ́wọ́.N óo máa mí túpetúpe,n óo máa mí hẹlẹhẹlẹ.