22 “Ẹ yipada sí mi kí á gbà yín là,gbogbo ẹ̀yin òpin ayé.Nítorí èmi ni Ọlọrun,kò tún sí ẹlòmíràn mọ́.
23 Mo ti fi ara mi búra,mo sì fi ẹnu mi sọ̀rọ̀ pẹlu òtítọ́ inú,ọ̀rọ̀ tí kò ní yipada:‘Gbogbo orúnkún ni yóo wólẹ̀ fún mi,èmi ni gbogbo eniyan yóo sì búra pé àwọn óo máa sìn.’
24 “Nípa èmi nìkan ni àwọn eniyan yóo máa pé,‘Ninu OLUWA ni òdodo ati agbára wà.’Gbogbo àwọn tí ń bá a bínúyóo pada wá sọ́dọ̀ rẹ̀ pẹlu ìtìjú.
25 Gbogbo àwọn ọmọ Israẹli yóo ṣẹgun,wọn yóo sì ṣògo ninu OLUWA.