1 “Oriṣa Bẹli tẹríba, oriṣa Nebo doríkodò.Orí àwọn ẹran ọ̀sìn ati mààlúù ni àwọn oriṣa wọn wà.Àwọn nǹkan tí ẹ̀ ń rù kiri wá di ẹrù, tí àwọn ẹranko tí ó ti rẹ̀ ń rù.
2 Àwọn mejeeji jọ tẹríba, wọ́n jọ doríkodò,wọn ò lè gba àwọn ẹrù wọn kalẹ̀.Àwọn pàápàá yóo lọ sí ìgbèkùn.
3 “Ẹ tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin ará ilé Jakọbu,ati gbogbo ará ilé Israẹli tí ó ṣẹ́kù;ẹ̀yin tí mo pọ̀n láti ọjọ́ tí wọ́n ti bi yín,tí mo sì gbé láti inú oyún.
4 Èmi náà ni, títí di ọjọ́ ogbó yín,n óo gbé yín títí tí ẹ óo fi hewú lórí.Èmi ni mo da yín, n óo sì máa tọ́jú yín,n óo máa gbé yín, n óo sì gbà yín là.