Aisaya 49:19-25 BM

19 “Dájúdájú ilẹ̀ rẹ tí ó ti di aṣálẹ̀,ati àwọn tí ó ti di ahoro,yóo kéré fún àwọn tí yóo máa gbé inú rẹ̀ tí ó bá yá,a óo sì lé àwọn tí ó pa ọ́ run jìnnà sí ọ.

20 Àwọn ọmọ tí o bí ní àkókò ìgbèkùn rẹyóo sọ ní etígbọ̀ọ́ rẹ pé,‘Ibí yìí kéré jù fún wa,fún wa ní àyè sí i láti máa gbé.’

21 O óo bèèrè lọ́kàn ara rẹ nígbà náà pé,‘Ta ni ó bí àwọn ọmọ wọnyi fún mi?Ṣebí àwọn ọmọ mi ti kú, mo ti yàgàn,mo sì lọ sí ìgbèkùn lóko ẹrú.Ta ni ó wá tọ́ àwọn wọnyi dàgbà?Ṣebí èmi nìkan ni mo ṣẹ́kù,níbo ni àwọn wọnyi ti wá?’ ”

22 OLUWA Ọlọrun ní,“Wò ó, n óo gbé ọwọ́ mi sókè sí àwọn orílẹ̀-èdè.N óo gbé àsíá mi sókè sí àwọn eniyan,wọn óo gbé àwọn ọmọ rẹ ọkunrin mọ́ àyà wọnwọn óo sì gbé àwọn ọmọ rẹ obinrin sí èjìká.

23 Àwọn ọba ni yóo máa tọ́jú rẹ bíi baba,àwọn ayaba yóo sì máa tọ́jú rẹ bí ìyá,ní ìdojúbolẹ̀ ni wọn óo máa tẹríba fún ọ,wọn óo sì máa pọ́n eruku ẹsẹ̀ rẹ lá.O óo wá mọ̀ nígbà náà pé èmi ni OLUWA,ojú kò ní ti àwọn tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé mi.”

24 Ǹjẹ́ a lè gba ìkógun lọ́wọ́ alágbára,tabi kí á gba òǹdè lọ́wọ́ òkúrorò eniyan?

25 OLUWA ní:“Bí ó bá tilẹ̀ ṣeéṣe láti gba òǹdè lọ́wọ́ alágbára,tabi láti gba ìkógun lọ́wọ́ òkúrorò eniyan.N óo bá àwọn tí ó ń bá ọ jà jà,n óo sì gba àwọn ọmọ rẹ là.