2 “Kí ló dé tí mo wá àwọn eniyan mi tí n kò rí ẹnìkan;mo pè, ẹnikẹ́ni kò dá mi lóhùn?Ṣé n kò lágbára tó láti rà wọ́n pada ni;àbí n kò lágbára láti gba ni là?Wò ó! Ìbáwí lásán ni mo fi gbẹ́ omi òkun,tí mo sì fi sọ odò tí ń ṣàn di aṣálẹ̀,omi wọn gbẹ,òùngbẹ gbẹ àwọn ẹja inú wọn pa,wọ́n kú, wọ́n sì ń rùn.
3 Mo da òkùnkùn bo ojú ọ̀run bí aṣọ,mo ṣe aṣọ ọ̀fọ̀ ní ìbora fún wọn.”
4 OLUWA Ọlọrun ti fi ọ̀rọ̀ ìmọ̀ sí mi lẹ́nu.Kí n lè mọ bí a tií gba àwọn tí ọkàn wọn rẹ̀wẹ̀sì níyànjú.Ojoojumọ ni ó ń ṣí mi létí láràárọ̀,kí n lè máa gbọ́rọ̀ bí àwọn akẹ́kọ̀ọ́.
5 OLUWA Ọlọrun ti ṣí mi létí,n kò sì ṣe oríkunkun,tabi kí n pada sẹ́yìn.
6 Mo tẹ́ ẹ̀yìn sílẹ̀ fún àwọn tí ń nani lẹ́gba;mo sì kọ ẹ̀rẹ̀kẹ́ sí àwọn tí ń fa eniyan ní irùngbọ̀n tu.N kò fojú pamọ́ nítorí ẹ̀gàn,bẹ́ẹ̀ ni n kò gbójú sá fún itọ́ títu síni lójú.
7 OLUWA Ọlọrun ń ràn mí lọ́wọ́,nítorí náà ojú kò tì mí;nítorí náà mo múra gírí,mo jẹ́ kí ojú mi le koko,mo sì mọ̀ pé ojú kò ní tì mí.
8 Ẹni tí yóo dá mi láre wà nítòsí,ta ló fẹ́ bá mi jà?Ta ló fẹ́ fi ẹ̀sùn kàn mí?Kí olúwarẹ̀ súnmọ́ tòsí mi,kí á jọ kojú ara wa?