2 Fẹ ààyè àgọ́ rẹ sẹ́yìn,sì jẹ́ kí aṣọ tí ó ta sórí ibùgbé rẹ gbòòrò sí i, má ṣẹ́wọ́ kù.Na okùn àgọ́ rẹ kí ó gùn,kí o sì kan èèkàn rẹ̀ mọ́lẹ̀ kí ó lágbára.
3 Nítorí o óo tàn kálẹ̀, sí apá ọ̀tún ati apá òsì,àwọn ọmọ rẹ yóo gba ìtẹ́ àwọn orílẹ̀-èdè,wọn óo sì máa gbé àwọn ìlú tí ó ti di ahoro.
4 Má bẹ̀rù nítorí ojú kò ní tì ọ́,má sì dààmú, nítorí a kì yóo dójú tì ọ́,nítorí o óo gbàgbé ìtìjú ìgbà èwe rẹ,o kò sì ní ranti ẹ̀sín ìgbà tí o jẹ́ opó mọ́.
5 Nítorí Ẹlẹ́dàá rẹ ni ọkọ rẹ,OLUWA àwọn ọmọ ogun ni orúkọ rẹ̀.Ẹni Mímọ́ Israẹli ni Olùràpadà rẹ,Ọlọrun gbogbo ayé ni à ń pè é.
6 Nítorí OLUWA ti pè ọ́,bí iyawo tí ọkọ rẹ̀ kọ̀ sílẹ̀, tí ọkàn rẹ̀ bàjẹ́,àní, bí iyawo àárọ̀ ẹni, tí a kọ̀ sílẹ̀;OLUWA ló sọ bẹ́ẹ̀.
7 Mo kọ̀ ọ́ sílẹ̀ fún ìgbà díẹ̀,ṣugbọn n óo kó ọ jọ pẹlu ọpọlọpọ àánú.
8 Mo fojú mi pamọ́ fún ọ,fún ìgbà díẹ̀ nítorí inú mi ń ru sí ọ,ṣugbọn nítorí ìfẹ́ àìlópin mi, n óo ṣàánú fún ọ.Èmi OLUWA, Olùràpadà rẹ ni mo sọ bẹ́ẹ̀.