8 Mo fojú mi pamọ́ fún ọ,fún ìgbà díẹ̀ nítorí inú mi ń ru sí ọ,ṣugbọn nítorí ìfẹ́ àìlópin mi, n óo ṣàánú fún ọ.Èmi OLUWA, Olùràpadà rẹ ni mo sọ bẹ́ẹ̀.
9 Bí ìgbà ayé Noa ni Ọ̀rọ̀ yìí rí sí mi:mo búra nígbà náà, pé omi Noa kò ní bo ayé mọ́lẹ̀ mọ́.Bẹ́ẹ̀ náà ni mo búra nisinsinyii,pé n kò ní bínú sí ọ mọ́,pé n kò ní bá ọ wí mọ́.
10 Bí àwọn òkè ńlá tilẹ̀ ṣí kúrò,tí a sì ṣí àwọn òkè kéékèèké nídìí,ṣugbọn ìfẹ́ mi tí kì í yẹ̀, kò ní yẹ̀ lára rẹ,majẹmu alaafia mi tí mo bá ọ dá kò ní yẹ̀.Èmi OLUWA tí mo ṣàánú fún ọ ni mo sọ bẹ́ẹ̀.
11 OLUWA ní:“Jerusalẹmu, ìwọ ẹni tí a pọ́n lójú, tí hílàhílo bá,tí a kò sì tù ninu,òkúta tí a fi oríṣìíríṣìí ọ̀dà kùn ni n óo fi kọ́ ọ,òkúta safire ni n óo sì fi ṣe ìpìlẹ̀ rẹ.
12 Òkúta Agate ni n óo fi ṣe ṣóńṣó ilé rẹ,òkúta dídán ni n óo fi ṣe ẹnu ọ̀nà ibodè rẹ,àwọn òkúta olówó iyebíye ni n óo fi mọ odi rẹ.
13 “Gbogbo àwọn ọmọ rẹ ọkunrin, ni OLUWA yóo kọ́wọn yóo sì ṣe ọpọlọpọ àṣeyọrí.
14 A óo fìdí rẹ múlẹ̀, ninu òdodo,o óo jìnnà sí ìnira, nítorí náà ẹ̀rù kò ní bà ọ́.O óo jìnnà sí ìpayà, nítorí kò ní súnmọ́ ọ.