4 Wò ó! Mo fi í ṣe olórí fún àwọn eniyan,olórí ati aláṣẹ àwọn orílẹ̀-èdè.
5 O óo pe àwọn orílẹ̀-èdè tí o kò mọ̀ rí,àwọn orílẹ̀-èdè tí kò mọ̀ ọ́ rí yóo sáré wá sọ́dọ̀ rẹ,nítorí OLUWA Ọlọrun rẹ,ati nítorí Ẹni Mímọ́ Israẹli, tí ó ṣe ọ́ lógo.”
6 Ẹ wá OLUWA nígbà tí ẹ lè rí i,ẹ pè é nígbà tí ó wà nítòsí.
7 Kí eniyan burúkú fi ọ̀nà ibi rẹ̀ sílẹ̀,kí alaiṣododo kọ èrò burúkú rẹ̀ sílẹ̀,kí ó yipada sí OLUWA,kí OLUWA lè ṣàánú rẹ̀.Kí ó yipada sọ́dọ̀ Ọlọrun wa,nítorí Ọlọrun yóo dáríjì í lọpọlọpọ.
8 OLUWA ní,“Nítorí èrò tèmi yàtọ̀ sí tiyín,bẹ́ẹ̀ ni ọ̀nà mi yàtọ̀ sí tiyín,
9 Bí ọ̀run ṣe ga ju ayé lọ,bẹ́ẹ̀ ni ọ̀nà mi ga ju ọ̀nà yín,tí èrò mi sì ga ju èrò yín.
10 “Bí òjò ati yìnyín, tí ń rọ̀ láti ojú ọ̀run,tí wọn kì í pada sibẹ mọ́,ṣugbọn tí wọn ń bomi rin ilẹ̀,tí ń mú kí nǹkan hù jáde;kí àgbẹ̀ lè rí èso gbìn,kí eniyan sì rí oúnjẹ jẹ.