Aisaya 58:1-6 BM

1 “Kígbe sókè, má dákẹ́,ké sókè bíi fèrè ogun,sọ ìrékọjá àwọn eniyan mi fún wọn ní àsọyé,sọ ẹ̀ṣẹ̀ ilé Jakọbu fún wọn.

2 Nítòótọ́ ni wọ́n ń wá mi lojoojumọ,wọ́n sì fẹ́ mọ ìlànà mi,wọ́n ṣe bí orílẹ̀-èdè tí ó mọ òdodo,tí kò kọ òfin Ọlọrun wọn sílẹ̀.Wọ́n ń bèèrè ìdájọ́ òdodo lọ́dọ̀ mi,wọ́n ní ìfẹ́ ati súnmọ́ Ọlọrun.”

3 Wọ́n ń bèèrè pé, “Kí ló dé tí à ń gbààwẹ̀, ṣugbọn tí OLUWA kò rí wa?Tí à ń fìyà jẹ ara wa, ṣugbọn tí kò náání wa?”OLUWA wí pé,“Ìdí rẹ̀ ni pé,nígbà tí ẹ bá ń gbààwẹ̀, ẹ̀ máa ṣe ìfẹ́ ọkàn yín.Ẹ̀ sì máa ni gbogbo àwọn òṣìṣẹ́ yín lára.

4 Ẹ̀ ń kún fún ìjà ati asọ̀ ní àkókò ààwẹ̀ yín,ẹ̀ ń lu ara yín ní ìlù ìkà.Irú ààwẹ̀ tí ẹ̀ ń gbà yìí kò ní jẹ́ kí Ọlọrun gbọ́ ohùn yín lọ́run.

5 Ṣé irú ààwẹ̀ tí mo yàn nìyí, ọjọ́ tí eniyan yóo rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ lásán?Ṣé kí eniyan lè doríkodò bíi koríko etí odò nìkan ni?Tabi kí ó lè jókòó lórí aṣọ ọ̀fọ̀ ati eérú nìkan?Ṣé èyí ni ẹ̀ ń pè ní ààwẹ̀, ati ọjọ́ tí ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà lọ́dọ̀ OLUWA?

6 “Ṣebí irú ààwẹ̀ tí mo yàn ni pé:kí á tú ìdè ìwà burúkú,kí á yọ irin tí a fi di igi àjàgà;kí á dá àwọn tí ìyà ń jẹ sílẹ̀ lọ́fẹ̀ẹ́,kí á já gbogbo àjàgà?