Aisaya 60:4-10 BM

4 Gbé ojú sókè kí o wò yíká,gbogbo wọn kó ara wọn jọ, wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ rẹ;àwọn ọmọ rẹ ọkunrin yóo wá láti òkèèrè,a óo sì gbé àwọn ọmọ rẹ obinrin lé apá wá.

5 Nígbà tí o bá rí wọn,inú rẹ yóo dùn,ara rẹ óo yá gágá.Ọkàn rẹ yóo kún fún ayọ̀,nítorí pé a óo gbé ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ọrọ̀ inú òkun wá sọ́dọ̀ rẹ.Àwọn orílẹ̀-èdè yóo kó ọrọ̀ wọn wá fún ọ.

6 Ogunlọ́gọ̀ ràkúnmí yóo yí ọ ká,àwọn ọmọ ràkúnmí Midiani ati Efa.Gbogbo àwọn tí wọn wà ní Ṣeba yóo wá,wọn óo mú wúrà ati turari wá;wọn óo sì máa pòkìkí OLUWA.

7 Gbogbo ẹran ọ̀sìn Kedari ni wọ́n óo kó wá fún ọ,wọn óo kó àgbò Nebaiotu wá ta ọ́ lọ́rẹ.Wọn óo jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà lórí pẹpẹ mi,ilé mi lógo, ṣugbọn n óo tún ṣe é lógo sí i.

8 Ta ni àwọn wọnyi tí ń fò lọ bí ìkùukùu?Bí ìgbà tí àwọn àdàbà bá ń fò lọ sí ibi ìtẹ́ wọn?

9 Nítorí àwọn erékùṣù yóo dúró dè mí,ọkọ̀ ojú omi Taṣiṣi ni yóo ṣiwajuwọn óo kó àwọn ọmọkunrin rẹ wá láti ilẹ̀ òkèèrè,wọn óo kó wúrà ati fadaka wá pẹlu wọn;nítorí orúkọ OLUWA Ọlọrun rẹ,ati Ẹni Mímọ́ Israẹli,nítorí ó ti ṣe ọ́ lógo.

10 OLUWA ní, “Àwọn àjèjì ni yóo máa tún odi rẹ mọ,àwọn ọba wọn yóo sì máa ṣe iranṣẹ fún ọ;nítorí pé inú ló bí mi ni mo fi nà ọ́.Ṣugbọn nítorí ojurere mi ni mo fi ṣàánú fún ọ.