1 “Ta ni ń ti Edomu bọ̀ yìí,tí ó wọ aṣọ àlàárì, tí ń bọ̀ láti Bosira,tí ó yọ bí ọjọ́ ninu aṣọ tí ó wọ̀,tí ń yan bọ̀ ninu agbára ńlá rẹ̀.”“Èmi ni, èmi tí mò ń kéde ẹ̀san,tí mo sì lágbára láti gbani là.”
2 “Kí ló dé tí aṣọ rẹ fi pupa,tí ó dàbí ti ẹni tí ń fún ọtí waini?”
3 OLUWA dáhùn, ó ní, “Èmi nìkan ni mo tí ń fún ọtí waini,ẹnikẹ́ni kò bá mi fún un ninu àwọn eniyan mi.Mo fi ibinu tẹ̀ wọ́n bí èso àjàrà,mo fi ìrúnú tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀.Ẹ̀jẹ̀ wọn bá dà sí mi láṣọ:ó ti di àbààwọ́n sára gbogbo aṣọ mi.
4 Nítorí ọjọ́ ẹ̀san ló wà lọ́kàn mi,ọdún ìràpadà mi sì ti dé.