6 Nítorí o ti ta àwọn eniyan rẹ nù,àní, ìdílé Jakọbu.Nítorí pé àwọn aláfọ̀ṣẹ ará ìhà ìlà oòrùn pọ̀ láàrin wọn,àwọn alásọtẹ́lẹ̀ sì pọ̀ bíi ti àwọn ará Filistini,Wọ́n ti gba àṣà àwọn àjèjì.
7 Wúrà ati fadaka kún ilẹ̀ wọn,ìṣúra wọn kò sì lópin.Ẹṣin kún ilẹ̀ wọn,kẹ̀kẹ́ ogun wọn kò sì lóǹkà.
8 Ilẹ̀ wọn kún fún oriṣa,wọ́n ń bọ iṣẹ́ ọwọ́ ara wọn,wọ́n ń wólẹ̀ fún ohun tí wọ́n fọwọ́ ara wọn ṣe.
9 Bẹ́ẹ̀ ni eniyan ṣe tẹ ara rẹ̀ lórí batí ó sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀.Oluwa, máṣe dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n.
10 Ẹ wọnú àpáta lọ,kí ẹ sì farapamọ́ sinu ilẹ̀.Ẹ sá fún ibinu OLUWAati ògo ọlá ńlá rẹ̀.
11 A óo rẹ ọlọ́kàn gíga eniyan sílẹ̀,a óo sì rẹ àwọn onigbeeraga sílẹ̀;OLUWA nìkan ni a óo gbéga ní ọjọ́ náà.
12 Nítorí OLUWA àwọn ọmọ ogun ti ya ọjọ́ kan sọ́tọ̀,tí yóo dojú ìjà kọ àwọn agbéraga,ati àwọn ọlọ́kàn gíga,ati gbogbo nǹkan tí à ń gbéga.